• Home
  • About Us
  • Contact Us
Tuesday, October 7, 2025
  • Home
  • News
  • Politics
  • Fanfare
  • Culture
  • Education
  • Entertainment
  • Health
  • Travel and Tourism
  • More
    • Editorial
    • Business
    • Crime and Security
    • Opinion
    • Sports
No Result
View All Result
  • Home
  • News
  • Politics
  • Fanfare
  • Culture
  • Education
  • Entertainment
  • Health
  • Travel and Tourism
  • More
    • Editorial
    • Business
    • Crime and Security
    • Opinion
    • Sports
No Result
View All Result
No Result
View All Result

MỌ̀RÌWÒ Ń Ṣ’Ẹ̀SỌ́ NÍNÚ ÌGBÁGÓ. PẸ̀LÚ Ẹ̀BÙ Ẹ̀YÍN TÓ BÁ ỌRỌ̀ AJÉ ILẸ̀ YÌÍ, SÍBẸ̀, ṢÈYÍ MÁKINDÉ TÚN Ń ṢE BẸBẸ…!

Peter Olajide by Peter Olajide
April 2, 2024
in Uncategorized
0
MỌ̀RÌWÒ Ń Ṣ’Ẹ̀SỌ́ NÍNÚ ÌGBÁGÓ.  PẸ̀LÚ Ẹ̀BÙ Ẹ̀YÍN TÓ BÁ ỌRỌ̀ AJÉ ILẸ̀ YÌÍ, SÍBẸ̀, ṢÈYÍ MÁKINDÉ TÚN Ń ṢE BẸBẸ…!
3.3k
VIEWS

You might also like

Ex-Oyo Deputy Speaker, Abdulwasi Musah, Congratulates Olubadan-designate, Oba Ladoja

OLUBADAN: Let’s Rally Behind And Support His Initiatives — Mogaji Olawale Junaid Charges Indigene, Congratulates Oba Ladoja On Birthday, Enthronement

September 27, 2025
Just In : Makinde Presents Staff, Certificate Of Office To Oba Rashidi Ladoja ( Arusa 1)

A New Era for Ibadan: Hon. Adeojo Hails Oba Ladoja’s Ascension

September 27, 2025

...To get all news updates, Join our WhatsApp Group (Click Here)

MỌ̀RÌWÒ Ń Ṣ’Ẹ̀SỌ́ NÍNÚ ÌGBÁGÓ. PẸ̀LÚ Ẹ̀BÙ Ẹ̀YÍN TÓ BÁ ỌRỌ̀ AJÉ ILẸ̀ YÌÍ, SÍBẸ̀, ṢÈYÍ MÁKINDÉ TÚN Ń ṢE BẸBẸ…!

By Aiyelabegan Baba Awo, a Member of the GSM Advocates

Ahun ń gbénú páká yọrí,
Ògòǹgò ń gbìyànjú gbórí àkìtàn sọrọ̀,
Ìgbín ń gbìyànjú, ó ń ṣọlá nínú ìkarahun,
Ìran àwọn èèrùn ń fìforítì gbágìyàn sọrọ̀.

Ọ̀tọ̀ làá jẹ̀pà,
Ọ̀tọ̀ làá jẹ̀ ‘mumu,
Ọ̀tọ̀ nifin,
Ọ̀tọ̀ nipa,
Láwùjọ obì àwọn Gómìnà lórílẹ̀ èdè yìí,
Òfùà Ṣèyí Mákindé, ọ̀tọ̀ ló wà!

Bí pápá ń jó lóko, mọ̀jàlà á délé sòfófó,
Ìràwè ní í ṣàpèjúwe ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn lẹ́gàn,
Aláwọ̀ méje ni ń ṣe ‘kéde òjò tí kò ní rọ̀ mọ́,
Àyà hẹ̀rìmọ̀ ní í ṣafihan akọni òmìrán,
Ẹ̀rẹ̀kẹ́ ńlá la fi í m’aya m’ọmọ ọdẹ,
Odó iyán ní í jùwe ìyàwó àgbẹ̀ kùàbà lábà!

Bí ohun gbogbo ṣe le koko tó nira,
Tí ara ń ro okùn ọrọ̀ ajé,
Tí ara kò rọ adìẹ ìnájà gbogbo nílẹ̀ yìí
Tí tàgbà tọmọdé ń já lanba láti yán an yọ,
Tí tarúgbó tomidan ilẹ̀ yìí ń pọ̀sẹ̀sẹ̀ láti borí làlúrí sànmọ́nì,
Ní ẹlẹ́yìnjú àánú ọmọ ‘Látúbọ̀sún bá dìde wùyà!
Ó ní lọ́rọ̀ afẹ́fẹ́,ọya ni ká bi,
Lọ́rọ̀ òjò, ká bi Ṣàngó léèrè,
Ìgbàyégbádùn àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́,
Ojúṣe òun ọmọ Májọlágbé ni!

Also Read:  New Year: May this year bring you success in all your endeavors., New Year Message from Hon Mogaji Akin Fagbemi

Ló bá gbètò kan àrà ọ̀tọ̀ kalẹ̀,
*SÉFÀ(SAFER)* ló pe ètò ọ̀hún,
ó ló di dandan kí gbogbo ọmọ tòun tolùgbé ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ ó wà nídẹ̀kùn.
Ètò oúnjẹ fún àwọn ìdílé tí kò rọ́wọ́ họrí jùlọ ní gbogbo ẹkùn ilẹ̀ yìí làkọ́kọ́
Ó ṣètò owó ribiribi fún ẹka ètò ìlera,
Ó gbówó nlá kalẹ̀ fáwọn àgbẹ̀ k’írè oko lè sùnwá bọ̀,
Ètò ẹ̀yàwó f’áwọn ìṣòwò
Àní kí ètò ọrọ̀ ajé ìpínlẹ̀ yìí lè rú gọ́gọ́,
Bẹ́ẹ̀ ló tún yawó fún ètò ìlera,
Ìpèsè ọkọ̀ ọ̀fẹ́ làkọ́kọ́, kó tó wá ṣètò owó ọkọ̀ tí kò gunpá fún gbogbo arìnrìnàjò nílùúsílùú nípìnlẹ̀ yìí.

Ètò owó ìrànwọ́ (wage Award) fún gbogbo òṣìṣẹ́ àtòsìsẹ́ fẹ̀yìntì ìpínlẹ̀ yìí tún ni àrà kàsíàrà!
Owó ọ̀hún ò sì tẹ̀tì,
Àní kò tẹ̀tì láti òsù mẹ́fà títí di àsìkò yìí rárá,
Èyí tó ń jẹ́ kí iṣẹ́ ó lọ geerege!

Nípìnlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti Mákindé,
Àwọn àgbẹ̀ wà SÉFÀ(SAFER),
Àwọn oníṣòwò wà SÉFÀ (SAFER),
Àwọn òṣìṣẹ́ àtòsìsẹ́ fẹ̀yìntì wà SÉFÀ (SAFER),
Ètò ìlera wà SÉFÀ (SAFER),
Kódà *SÉFÀ(SAFER)* ni gbogbo olùgbé ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ wà!

Ṣèyí tún pèsè ààyè oorun, oúnjẹ, àti ètò ìlera ọ̀fẹ́,
Àní fáwọ̀n tí làlúrí dé bá nínú ìjàm̀bá Ìbúgbàmù àbaadì ní Bódìjà,
Títí dàsìkò yìí, lórí ọ̀rọ̀ wọn
Ọmọ Mákindé ó jẹ́ ó rẹ̀ un,
Ó ní ọ̀rán tó bá bá àwòrò ti kan irúnmọlẹ̀ lábùkù!

Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ mi, Ayélabẹ́gàn Àlàó,
A dúpẹ́ pé a ò bẹ kanlékanlé lásọ rán,
A ò bẹ bíríkìlà nílé kùn,
A ò bẹ onígbàjámọ̀ pé kó bá wa túnlẹ̀kùn tó bàjẹ́ ṣe,
Nípìnlẹ̀ Ọ̀yọ́,
Ìka tó tọ́ símú la fi remú,
Aláàánú la yàn sípò àtàtà,
Olúwa ló Ṣèyí fún wa l’Ọ́yọ̀ọ́,
A mọ̀n ọ́n lóore o……!

Also Read:  LG Oyo Poll: Hon. Rahman Adepoju of Ibadan North West Receives Certificate of Return From OYSIEC, FELICITATES WITH CONSTITUENTS:

© Ayélabẹ́gàn Akínkúnmi Abbas,
Ọ̀kan gbòógì nínú ẹgbẹ́ GSM advocate,
Ìwọ̀ Oòrùn Ọ̀yọ́,
Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́

08134856062


You can get every of our news as soon as they drop on WhatsApp ...To get all news updates, Join our WhatsApp Group (Click Here)
Previous Post

Wike, Fayose, Ortom may be indicted as PDP state chairmen vow to name anti-party figures

Next Post

Meet Engr. Akeem Olatunji Known As SARSINO |By Adedapo Alade Akilapa

Peter Olajide

Peter Olajide

Related Stories

Ex-Oyo Deputy Speaker, Abdulwasi Musah, Congratulates Olubadan-designate, Oba Ladoja

OLUBADAN: Let’s Rally Behind And Support His Initiatives — Mogaji Olawale Junaid Charges Indigene, Congratulates Oba Ladoja On Birthday, Enthronement

by Peter Olajide
September 27, 2025
0

  In a grand display of respect and admiration, Chief Oluwafemi Olawale Junaid, the esteemed Mogaji Jinadu Ile Ganga of...

Just In : Makinde Presents Staff, Certificate Of Office To Oba Rashidi Ladoja ( Arusa 1)

A New Era for Ibadan: Hon. Adeojo Hails Oba Ladoja’s Ascension

by Peter Olajide
September 27, 2025
0

    The Chairman of Ido Local Government, Hon. Sheriff Aderemi Adeojo, has extended a warm and heartfelt congratulatory message...

Globalcom Pays Courtesy Visit to Oyo Agency for Youth Development, Seeks Partnership on Enterprise Business Unit

Oyo Lawmaker, Hon. Babalola Abiodun Ph.D, Felicitates Oba Ladoja at 81, Describes New Olubadan as a Legend in the History of Ibadan and Oyo State

by Peter Olajide
September 25, 2025
0

  A prominent lawmaker in Oyo State, Hon. Babalola Abiodun Ph.D, has joined family members, political associates, and the people...

First Leg: Rwanda Vs Falconets, Oyo Commissioner Wishes Team Success, Assures Readiness of Oyo Government for Second Leg

Hon. Engr. Toheeb Adegoke Adlat Hails New PDP Leadership in Akinyele and Lagelu, Commends Party Unity and Grassroots Renewal

by Peter Olajide
September 21, 2025
0

    I, Hon. Engr. Toheeb Adegoke Adlat, Federal House of Representatives hopeful for Akinyele/Lagelu Federal Constituency, warmly congratulate the...

Next Post
Meet Engr. Akeem Olatunji Known As SARSINO |By Adedapo Alade Akilapa

Meet Engr. Akeem Olatunji Known As SARSINO |By Adedapo Alade Akilapa

Recommended

November:Ur’image Couture Head2Toe Set to Define Fashion Trends for Oyo State

November:Ur’image Couture Head2Toe Set to Define Fashion Trends for Oyo State

November 1, 2024
Ibadan North By-election: PDP Flags Off Campaign in Bodija as Governor Makinde Declares August 16 a DonDeal

Ibadan North By-election: PDP Flags Off Campaign in Bodija as Governor Makinde Declares August 16 a DonDeal

August 5, 2025

Popular Story

  • Breaking: Ibadan North Rep Member, Akinremi Dies

    Breaking: Ibadan North Rep Member, Akinremi Dies

    1050 shares
    Share 420 Tweet 263
  • Oyo Ad-hoc Staff Appeal to Governor Makinde

    962 shares
    Share 385 Tweet 241
  • Jubilation As Makinde Pays December Salaries Early

    883 shares
    Share 353 Tweet 221
  • Breaking: Ex Oyo Lawmaker, Hon Babatunde Eesuola is dead.

    871 shares
    Share 348 Tweet 218
  • Breaking : Two Years After Becoming Olubadan, Oba Balogun Joins Ancestors At 82

    864 shares
    Share 346 Tweet 216

Stay up-to-date with the latest happenings in Oyo State! From breaking news to in-depth updates on local events, our blog covers it all. Visit us regularly to stay informed about everything that matters in your community

  • Home
  • About Us
  • Contact Us

© 2024 Naija24hrs - Website Designed by Samtech Media (+2348103682435)

No Result
View All Result
  • Home
  • News
  • Politics
  • Fanfare
  • Culture
  • Education
  • Entertainment
  • Health
  • Travel and Tourism
  • Editorial
  • Crime and Security
  • Business
  • Opinion
  • Sports

© 2024 Naija24hrs - Website Designed by Samtech Media (+2348103682435)

Are you sure want to unlock this post?
Unlock left : 0
Are you sure want to cancel subscription?