• Home
  • About Us
  • Contact Us
Friday, November 21, 2025
  • Home
  • News
  • Politics
  • Fanfare
  • Culture
  • Education
  • Entertainment
  • Health
  • Travel and Tourism
  • More
    • Editorial
    • Business
    • Crime and Security
    • Opinion
    • Sports
No Result
View All Result
  • Home
  • News
  • Politics
  • Fanfare
  • Culture
  • Education
  • Entertainment
  • Health
  • Travel and Tourism
  • More
    • Editorial
    • Business
    • Crime and Security
    • Opinion
    • Sports
No Result
View All Result
No Result
View All Result

MỌ̀RÌWÒ Ń Ṣ’Ẹ̀SỌ́ NÍNÚ ÌGBÁGÓ. PẸ̀LÚ Ẹ̀BÙ Ẹ̀YÍN TÓ BÁ ỌRỌ̀ AJÉ ILẸ̀ YÌÍ, SÍBẸ̀, ṢÈYÍ MÁKINDÉ TÚN Ń ṢE BẸBẸ…!

Peter Olajide by Peter Olajide
April 2, 2024
in Uncategorized
0
MỌ̀RÌWÒ Ń Ṣ’Ẹ̀SỌ́ NÍNÚ ÌGBÁGÓ.  PẸ̀LÚ Ẹ̀BÙ Ẹ̀YÍN TÓ BÁ ỌRỌ̀ AJÉ ILẸ̀ YÌÍ, SÍBẸ̀, ṢÈYÍ MÁKINDÉ TÚN Ń ṢE BẸBẸ…!
3.3k
VIEWS

You might also like

Birthday: Oluyole LG chairman hails AKT’s contributions to democratic governance, Oyo’s socioeconomic dev

Engr. Toheeb Adegoke Celebrates Hon. Akintunde Olajide AKT, a Distinguished Voice for Lagelu at the Oyo State House of Assembly

November 19, 2025
Oyo Lawmaker, Hon. Wale Canada, Celebrates Engr. Popoola Olawale, GMD Highbridge Group, on His Birthday

Oyo Lawmaker, Hon. Wale Canada, Celebrates Engr. Popoola Olawale, GMD Highbridge Group, on His Birthday

November 10, 2025

...To get all news updates, Join our WhatsApp Group (Click Here)

MỌ̀RÌWÒ Ń Ṣ’Ẹ̀SỌ́ NÍNÚ ÌGBÁGÓ. PẸ̀LÚ Ẹ̀BÙ Ẹ̀YÍN TÓ BÁ ỌRỌ̀ AJÉ ILẸ̀ YÌÍ, SÍBẸ̀, ṢÈYÍ MÁKINDÉ TÚN Ń ṢE BẸBẸ…!

By Aiyelabegan Baba Awo, a Member of the GSM Advocates

Ahun ń gbénú páká yọrí,
Ògòǹgò ń gbìyànjú gbórí àkìtàn sọrọ̀,
Ìgbín ń gbìyànjú, ó ń ṣọlá nínú ìkarahun,
Ìran àwọn èèrùn ń fìforítì gbágìyàn sọrọ̀.

Ọ̀tọ̀ làá jẹ̀pà,
Ọ̀tọ̀ làá jẹ̀ ‘mumu,
Ọ̀tọ̀ nifin,
Ọ̀tọ̀ nipa,
Láwùjọ obì àwọn Gómìnà lórílẹ̀ èdè yìí,
Òfùà Ṣèyí Mákindé, ọ̀tọ̀ ló wà!

Bí pápá ń jó lóko, mọ̀jàlà á délé sòfófó,
Ìràwè ní í ṣàpèjúwe ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn lẹ́gàn,
Aláwọ̀ méje ni ń ṣe ‘kéde òjò tí kò ní rọ̀ mọ́,
Àyà hẹ̀rìmọ̀ ní í ṣafihan akọni òmìrán,
Ẹ̀rẹ̀kẹ́ ńlá la fi í m’aya m’ọmọ ọdẹ,
Odó iyán ní í jùwe ìyàwó àgbẹ̀ kùàbà lábà!

Bí ohun gbogbo ṣe le koko tó nira,
Tí ara ń ro okùn ọrọ̀ ajé,
Tí ara kò rọ adìẹ ìnájà gbogbo nílẹ̀ yìí
Tí tàgbà tọmọdé ń já lanba láti yán an yọ,
Tí tarúgbó tomidan ilẹ̀ yìí ń pọ̀sẹ̀sẹ̀ láti borí làlúrí sànmọ́nì,
Ní ẹlẹ́yìnjú àánú ọmọ ‘Látúbọ̀sún bá dìde wùyà!
Ó ní lọ́rọ̀ afẹ́fẹ́,ọya ni ká bi,
Lọ́rọ̀ òjò, ká bi Ṣàngó léèrè,
Ìgbàyégbádùn àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́,
Ojúṣe òun ọmọ Májọlágbé ni!

Also Read:  Oluwo, Chief Lekan Alabi, Hon. Oduyoye Attend As Euro Lounge Chairman, Mogaji Busari, Receives RATTAWU Award In Ibadan

Ló bá gbètò kan àrà ọ̀tọ̀ kalẹ̀,
*SÉFÀ(SAFER)* ló pe ètò ọ̀hún,
ó ló di dandan kí gbogbo ọmọ tòun tolùgbé ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ ó wà nídẹ̀kùn.
Ètò oúnjẹ fún àwọn ìdílé tí kò rọ́wọ́ họrí jùlọ ní gbogbo ẹkùn ilẹ̀ yìí làkọ́kọ́
Ó ṣètò owó ribiribi fún ẹka ètò ìlera,
Ó gbówó nlá kalẹ̀ fáwọn àgbẹ̀ k’írè oko lè sùnwá bọ̀,
Ètò ẹ̀yàwó f’áwọn ìṣòwò
Àní kí ètò ọrọ̀ ajé ìpínlẹ̀ yìí lè rú gọ́gọ́,
Bẹ́ẹ̀ ló tún yawó fún ètò ìlera,
Ìpèsè ọkọ̀ ọ̀fẹ́ làkọ́kọ́, kó tó wá ṣètò owó ọkọ̀ tí kò gunpá fún gbogbo arìnrìnàjò nílùúsílùú nípìnlẹ̀ yìí.

Ètò owó ìrànwọ́ (wage Award) fún gbogbo òṣìṣẹ́ àtòsìsẹ́ fẹ̀yìntì ìpínlẹ̀ yìí tún ni àrà kàsíàrà!
Owó ọ̀hún ò sì tẹ̀tì,
Àní kò tẹ̀tì láti òsù mẹ́fà títí di àsìkò yìí rárá,
Èyí tó ń jẹ́ kí iṣẹ́ ó lọ geerege!

Nípìnlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti Mákindé,
Àwọn àgbẹ̀ wà SÉFÀ(SAFER),
Àwọn oníṣòwò wà SÉFÀ (SAFER),
Àwọn òṣìṣẹ́ àtòsìsẹ́ fẹ̀yìntì wà SÉFÀ (SAFER),
Ètò ìlera wà SÉFÀ (SAFER),
Kódà *SÉFÀ(SAFER)* ni gbogbo olùgbé ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ wà!

Ṣèyí tún pèsè ààyè oorun, oúnjẹ, àti ètò ìlera ọ̀fẹ́,
Àní fáwọ̀n tí làlúrí dé bá nínú ìjàm̀bá Ìbúgbàmù àbaadì ní Bódìjà,
Títí dàsìkò yìí, lórí ọ̀rọ̀ wọn
Ọmọ Mákindé ó jẹ́ ó rẹ̀ un,
Ó ní ọ̀rán tó bá bá àwòrò ti kan irúnmọlẹ̀ lábùkù!

Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ mi, Ayélabẹ́gàn Àlàó,
A dúpẹ́ pé a ò bẹ kanlékanlé lásọ rán,
A ò bẹ bíríkìlà nílé kùn,
A ò bẹ onígbàjámọ̀ pé kó bá wa túnlẹ̀kùn tó bàjẹ́ ṣe,
Nípìnlẹ̀ Ọ̀yọ́,
Ìka tó tọ́ símú la fi remú,
Aláàánú la yàn sípò àtàtà,
Olúwa ló Ṣèyí fún wa l’Ọ́yọ̀ọ́,
A mọ̀n ọ́n lóore o……!

Also Read:  Oluyole LG Chairman-elect, Akeem Olatunji Announces Transition C'tee Members

© Ayélabẹ́gàn Akínkúnmi Abbas,
Ọ̀kan gbòógì nínú ẹgbẹ́ GSM advocate,
Ìwọ̀ Oòrùn Ọ̀yọ́,
Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́

08134856062


You can get every of our news as soon as they drop on WhatsApp ...To get all news updates, Join our WhatsApp Group (Click Here)
Previous Post

Wike, Fayose, Ortom may be indicted as PDP state chairmen vow to name anti-party figures

Next Post

Meet Engr. Akeem Olatunji Known As SARSINO |By Adedapo Alade Akilapa

Peter Olajide

Peter Olajide

Related Stories

Birthday: Oluyole LG chairman hails AKT’s contributions to democratic governance, Oyo’s socioeconomic dev

Engr. Toheeb Adegoke Celebrates Hon. Akintunde Olajide AKT, a Distinguished Voice for Lagelu at the Oyo State House of Assembly

by Peter Olajide
November 19, 2025
0

  Engr. Toheeb Adegoke extends his warmest birthday wishes to Hon. Akintunde Olajide AKT, the esteemed representative of Lagelu Constituency...

Oyo Lawmaker, Hon. Wale Canada, Celebrates Engr. Popoola Olawale, GMD Highbridge Group, on His Birthday

Oyo Lawmaker, Hon. Wale Canada, Celebrates Engr. Popoola Olawale, GMD Highbridge Group, on His Birthday

by Peter Olajide
November 10, 2025
0

  The lawmaker representing Atisbo/Saki-East State Constituency and Chairman, House Committee on Health, Oyo State House of Assembly, Hon. Saminu...

JAO commends Gov Makinde, Deputy on Igboho-Kishi road reconstruction

JAO commends Gov Makinde, Deputy on Igboho-Kishi road reconstruction

by Peter Olajide
November 6, 2025
0

  JIMOH Adisa Olabisi from Oorelope Local Government Area, has expressed deep appreciation to the Executive Governor of Oyo State,...

Egbeda Council Chairman, Sanda Presents Patrol Vehicle to Egbeda Police Station

HON. SHERIFF ADEOJO HONOURED WITH “ICON OF LOCAL GOVERNMENT ADMINISTRATION AWARD”

by Peter Olajide
November 6, 2025
0

The Executive Chairman of Ido Local Government, Hon. Sheriff Aderemi Adeojo, has been honoured with the prestigious award, “Icon of...

Next Post
Meet Engr. Akeem Olatunji Known As SARSINO |By Adedapo Alade Akilapa

Meet Engr. Akeem Olatunji Known As SARSINO |By Adedapo Alade Akilapa

Recommended

Breaking: Makinde Gifts New Utility Vehicle to Olopoeyan

Breaking: Makinde Gifts New Utility Vehicle to Olopoeyan

May 21, 2025
Birthday: Ibarapa North chair, Akorede Lateef Celebrates with Vice Chairman Hon Olubisi Akande on his birthday 

Birthday: Ibarapa North chair, Akorede Lateef Celebrates with Vice Chairman Hon Olubisi Akande on his birthday 

June 27, 2025

Popular Story

  • Breaking: Ibadan North Rep Member, Akinremi Dies

    Breaking: Ibadan North Rep Member, Akinremi Dies

    1063 shares
    Share 425 Tweet 266
  • Oyo Ad-hoc Staff Appeal to Governor Makinde

    965 shares
    Share 386 Tweet 241
  • Jubilation As Makinde Pays December Salaries Early

    885 shares
    Share 354 Tweet 221
  • Breaking: Ex Oyo Lawmaker, Hon Babatunde Eesuola is dead.

    876 shares
    Share 350 Tweet 219
  • Breaking : Two Years After Becoming Olubadan, Oba Balogun Joins Ancestors At 82

    866 shares
    Share 346 Tweet 217

Stay up-to-date with the latest happenings in Oyo State! From breaking news to in-depth updates on local events, our blog covers it all. Visit us regularly to stay informed about everything that matters in your community

  • Home
  • About Us
  • Contact Us

© 2024 Naija24hrs - Website Designed by Samtech Media (+2348103682435)

No Result
View All Result
  • Home
  • News
  • Politics
  • Fanfare
  • Culture
  • Education
  • Entertainment
  • Health
  • Travel and Tourism
  • Editorial
  • Crime and Security
  • Business
  • Opinion
  • Sports

© 2024 Naija24hrs - Website Designed by Samtech Media (+2348103682435)

Are you sure want to unlock this post?
Unlock left : 0
Are you sure want to cancel subscription?